Ní’gbà tí Olóyè MKO Abíọ́lá kú, ní ọjọ́ kéje, oṣù kéje, ọdún 1998, a mọ̀ wípé wọ́n fun ní tea mu, Susan Rice, òṣ’iṣẹ́ fún ìjọba America sì pẹ̀lú àwọn tí wọn jọ wa ní’bẹ̀, pẹ̀lú àwọn ìjọba ol’ógun Nigeria.

Orílẹ̀-Èdè Yorùbá jẹ́ Orílẹ̀-Èdè Olómìnira ti ara rẹ̀. Gbogbo ìgbésẹ̀ tí orílẹ̀-èdè Nigerí àti àwọn gómìnà Nigeria, tí wọ́n ngbé l’orílẹ̀-èdè Yorùbá, gbogbo ẹ̀ pátápátá l’a nkójọ pọ̀ gẹ́gẹ́bí ẹ̀rí.Olori Adele Orílẹ̀-Èdè Yorùbá, 

Ọgbeni Mobọlaji Ọlawale Akinọla Ọmọkore
Lies about the death of MKO Abiola

A kìí ṣe ọmọdé, bẹ́ẹ̀ ni a kìí ṣe ọ̀dẹ̀; kò s’ẹni bé’rè ẹjọ́ l’ọwọ́ Susan Rice, èyí tí ó fi wá nsọ mọ́namọ̀na nínú ìwé itan ìgbésí ayé rẹ̀ wípé kìí ṣe ni wọ́n pa Abíọ́lá.

Ó ṣeun gan-an ni o, a ò bérè ẹjọ́ l’ọwọ́ rẹ̀ rárá.

Nṣe ni k’ó kó gbogbo wàhálà t’ó dé báa ẹ kúrò ní sàkání tiwa.

Ka Ìròyìn: Àwọn Òyìnbó, Aláyébàjẹ́ Ni Wọ́n

Ìwọ kọ́ l’ó máa sọ ìtàn bí Abíọ́lá ṣe kú fún’wa. A ní ìtàn ti’wa nípa bí wọ́n ṣe pa Abíọ́lá.

Ayé àtijọ́ ni òyínbó ti máa np’ìtàn ìran Yorùbá fún Yorùbá. Ní’si’ìyí, aṣọ ìbòjú ti kúrò l’ojú wa; ati wá kúrò l’oko ẹrú pátápátá l’abẹ́ òyìnbó.

Aláìnítìjú t’ó nsá pamọ́ s’ẹhìn ìka kan.

Olori Adele of the democratic republic of the Yoruba government address to indigenous yoruba people

Ka Ìròyìn: Tí o bá fẹ́ sọ ẹ̀yàk’ẹyà di ẹrú, gba èdè àti ìtàn wọn – Wendall Donelson

Democratic republic of the Yoruba iroyin ojo'jumo